Go to full page →

Ṣe Ìnáání àwọn Èrúnrún IIO 154

Nínú iṣẹ́ ìyanu ti bíbọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ pẹ̀lú ìṣù àkàrà díẹ̀ àti ẹja, oúnjẹ náà ń pọ̀ sí i bí ó ṣe ń kọjá láti ọ̀dọ̀ ọ Krístì lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ó gbà á. Báyìí yóò wà nínú fífọ́n káàkiri. Òtítọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run bí a ṣe ń gbé e ká yóò di púpọ̀ sí i lọ́pọ̀lọpọ̀. Bí ọmọ ẹ̀yìn Krístì nípa ìdari Kristi ṣe kó àwọn àjẹkù jọ, kí ohunkóhun má ba à ṣègbé, bákan náà, a gbọdọ̀ ṣe ìṣúra ọ̀kọ̀ọ̀kan ìwé tí a jẹ kù tí ó kún fún òtítọ́ ọ ti àsìkò yìí. Kò sí ẹni tí ó lè ṣe ìdíyelé ipa tí ojú ewé tí a ya dànù pàápàá tí ó kún fún àwọn òtítọ́ ọ ti iṣẹ́ ìránṣẹ́ ańgẹ́lì kẹ́ta le è ní lórí ọkàn àwọn díẹ̀ tí wọ́n ń wá òtítọ́.- Southern Watchmann, Jan.5, 1904. IIO 154.1